35. Èyí ni ohun tí Ọlọ́run alágbára sọ:“Wò ó, èmi yóò fọ́ ìtẹ̀gùn Élámù,ẹni tí wọ́n sinmi lé nípa agbára.
36. Èmi yóò mú kí afẹ́fẹ́ orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rinàgbáyé lòdì sí Élámù.Èmi yóò tú wọn ká sí ìpín afẹ́fẹ́ mẹ́rinàti pé, kò sí orílẹ̀ èdè tí ilẹ̀ àjèjì Élámù kò ní lọ.
37. Èmi yóò kẹ́gàn Élámù lójúàwọn ọ̀tá rẹ̀ àti lọ́dọ̀ àwọntí wọ́n jọ ń gbé.Èmi yóò mú ibi wá sí orí wọn,pàápàá ìbínú gbígbóná mi;”bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.“Èmi yóò lé wọn pẹ̀lú idà, di ìgbà tí èmi yóò rẹ́yìn wọn.