Jẹ́nẹ́sísì 50:18-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Àwọn arákùnrin rẹ̀ wá, wọ́n sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, wọ́n wí pé, “Ẹrú rẹ ni a jẹ́.”

19. Ṣùgbọ́n Jósẹ́fù wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù, èmi ha wà ní ipò Ọlọ́run bí?

20. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ gbérò láti ṣe mi ní ibi, ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbérò láti fi ṣe rere tí ń ṣe lọ́wọ́ yìí; ni gbígba ẹ̀mi ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn là.

21. Nítorí náà, ẹ má ṣe bẹ̀rù. Èmi yóò pèṣè fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín.” Ó tún fi wọ́n lọ́kàn balẹ̀, ó sì sọ ọ̀rọ̀ rere fun wọn.

22. Jósẹ́fù sì ń gbé ní Éjíbítì pẹ̀lú gbogbo ìdílé baba rẹ̀. Ó sì wà láàyè fún àádọ́fà (110) ọdún.

23. Ó sì rí ìran kẹta ọmọ Éfúrémù-Àwọn ọmọ Mákírì, ọmọkùnrin Mánásè ni a sì gbé le eékún Jósẹ́fù nígbà tí ó bí wọn.

24. Nígbà náà ni Jóṣẹ́fù wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Mo ti fẹrẹ kú, ṣùgbọ́n dájúdájú Ọlọ́run yóò wá sí ìrànlọ́wọ́ yín, yóò sì mú-un yín jáde kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí ó ti ṣèlérí ní ìbúra fún Ábúráhámù, Ísáákì àti Jákọ́bù.”

Jẹ́nẹ́sísì 50