Jẹ́nẹ́sísì 5:24-32 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Énọ́kù bá Ọlọ́run rìn: a kò sì rí i mọ́ nítorí Ọlọ́run mú un lọ.

25. Nígbà tí Mètúsẹ́là pé igba-ó-dín-mẹ́talá ọdún (187) ní o bí Lámékì.

26. Lẹ́yìn èyí ó wà láàyè fún ẹgbẹ̀rin-dín-méjìdínlógún ọdún (782), ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin.

27. Àpapọ̀ ọdún Mètúsẹ́là jẹ́ ẹgbẹ̀rún-ọdún-ó-dín-mọ́kànlélọ́gbọ̀n (969), ó sì kú.

28. Nígbà tí Lámékì pé ọdún méjìlélọ́gọ́sàn án (182) ni ó bí ọmọkùnrin kan.

29. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Nóà, ó sì wí pé, “Eléyìí ni yóò tù wá nínú ni iṣẹ́ àti làálàá ọwọ́ wa, nítorí ilẹ̀ tí Ọlọ́run ti fi gégùn-ún.”

30. Lẹ́yìn tí ó bí Nóà, Lámékì gbé fún ẹgbẹ̀ta-ó-dín-márùn-ún ọdún (595), ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin.

31. Àpapọ̀ ọdún rẹ̀ sì jẹ́ ẹgbẹ̀rin-ọdún-ó-dín-mẹ́talélógún (777), ó sì kú.

32. Lẹ́yìn tí Nóà pé ọmọ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ọdún (500) ni ó bí Ṣémù, Ámù àti Jáfétì.

Jẹ́nẹ́sísì 5