Jẹ́nẹ́sísì 47:29-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

29. Nígbà tí àkókò ń súnmọ́ etílé fún Ísírẹ́lì láti kú, ó pe Jósẹ́fù, ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún-un pé, “Bí mo bá rí ojú rere ni oju rẹ̀ fi ọwọ́ rẹ sí abẹ́ itan mi, kí o sì ṣe ìlérí pé ìwọ yóò fi àánú àti òtítọ́ hàn sí mi. Má ṣe sin òkú mi sí ilẹ̀ Éjíbítì,

30. Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo bá sinmi pẹ̀lú àwọn baba mi, gbé mí jáde kúrò ní Éjíbítì kí o sì sin mí sí ibi tí wọ́n sin àwọn baba mi sí.”Jóṣẹ́fù sì dáhùn wí pé, “Èmi ó ṣe bí ìwọ ti wí.”

31. Jákọ́bù wí pé, “Búra fún mi,” Jósẹ́fù sì búra fún un. Ísírẹ́lì sì tẹ orí rẹ̀ ba, bí ó ti sinmi lé ori ìbùsùn rẹ̀.

Jẹ́nẹ́sísì 47