Jẹ́nẹ́sísì 46:19-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Àwọn ọmọkùnrin Rákélì aya Jákọ́bù:Jósẹ́fù àti Bẹ́ńjámínì.

20. Ní Éjíbiti, Áṣénátù ọmọbìnrin Pọ́tíférà, alábojútó àti àlùfáà Ónì, bí Mánásè àti Éfúráímù fún Jósẹ́fù.

21. Àwọn ọmọ Bẹ́ńjámínì:Bélà, Békérì, Áṣíbélì, Gérà, Náámánì, Éhì, Rósì, Múpímù, Húpímù àti Árídà.

22. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Rákẹ́lì bí fún Jákọ́bù. Wọ́n jẹ́ mẹ́rìnlá (14) lápapọ̀.

23. Àwọn ọmọ Dánì:Úsímù.

24. Àwọn ọmọ Náfítalì:Jáháṣíè, Gúnì, Jésérì, àti Ṣílémù.

25. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ tí Bílíhà ẹni tí Lábánì fi fún Rákélì ọmọ rẹ̀ bí fún Jákọ́bù. Wọ́n jẹ́ méje lápapọ̀.

26. Gbogbo àwọn tí ó lọ pẹ̀lú Jákọ́bù sí Éjíbítì, àwọn tí ó jẹ́ ìran rẹ̀ tààrà láì ka àwọn aya ọmọ rẹ̀, jẹ́ ènìyàn mẹ́rìndín-ní-àadọ́rin (66).

Jẹ́nẹ́sísì 46