8. Báyìí ni Ísọ̀ tí a tún mọ̀ sí Édómù tẹ̀dó sí àwọn orílẹ̀ èdè oloke tí Ṣéírì.
9. Èyí ni ìran Ísọ̀ baba àwọn ará Édómù ní àwọn orílẹ̀ èdè olókè Ṣéírì.
10. Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Ísọ̀:Élífásì ọmọ Ádà aya Ísọ̀ àti Rúélì, ọmọ Báṣémátì tí í ṣe aya Ísọ̀ pẹ̀lú.
11. Àwọn ọmọ Élífásì ni ìwọ̀nyí:Témánì, Ómárì, Ṣéfò, Gátamù, àti Kénásì.
12. Élífásì ọmọ Ísọ̀ sì tún ní àlè tí a ń pè ní Tímúnà pẹ̀lú, òun ló bí Ámálékì fún un. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ-ọmọ Ádà aya Ísọ̀.