Jẹ́nẹ́sísì 35:20-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Jákọ́bù sì mọ òpó (ọ̀wọ̀n) kan sí ibojì rẹ̀, òpó náà sì tọ́ka sí ojú ibojì Rákélì títí di òní.

21. Ísírẹ́lì sì ń bá ìrìn-àjò rẹ̀ lọ, ó sì pa àgọ́ rẹ̀ sí Migida-Édérì (ilé-ìsọ́ Édérì).

22. Nígbà tí Ísírẹ́lì sì ń gbé ní ibẹ̀, Rúbẹ́nì wọlé tọ Bílíhà, àlè (ìyàwó tí a kò fi owó fẹ́ lọ́wọ́ àwọn òbí rẹ̀) baba rẹ̀ lọ, ó sì bá a lò pọ̀, Ísírẹ́lì sì gbọ́ ọ̀rọ̀ náà.Jákọ́bù sì bí ọmọkunrin méjìlá:

23. Àwọn ọmọ Líà:Rúbẹ́nì tí í ṣe àkọ́bí Jákọ́bù,Símónì, Léfì, Júdà, Ísákárì àti Ṣébúlúnì.

24. Àwọn ọmọ Rákélì:Jóṣẹ́fù àti Bẹ́ńjámínì.

25. Àwọn ọmọ Bílíhà ìránṣẹ́bìnrin Rákélì:Dánì àti Náfítalì.

26. Àwọn ọmọ Ṣílípà ìránṣẹ́-bìnrin Líà:Gádì àti Áṣérì.Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ tí Jákọ́bù bí ní Padani-Árámù.

27. Jákọ́bù sì padà dé ilé lọ́dọ̀ Ísáákì baba rẹ̀ ni Mámúrè ní tòsí i Kiriati-Árábà (Hébúrónì). Níbi tí Ábúráhámù àti Ísáákì gbé.

28. Ẹni ọgọ́sán-an (180) ọdún ni Ísáákì.

29. Ísáákì sì kú láìpẹ́ lẹ́yìn ìpadàbọ̀ Jákọ́bù, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ̀ ní ọjọ́-ogbó rẹ̀. Ísọ̀ àti Jákọ́bù ọmọ rẹ̀ sì sin-ín.

Jẹ́nẹ́sísì 35