Ísíkẹ́lì 4:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Nísinsìnyìí, Ìwọ ọmọ ènìyàn, mú amọ̀ ṣíṣù kan, gbé e sí iwájú rẹ, kí o sì ya àwòrán Jérúsálẹ́mù sí orí rẹ̀.

2. Kí o sì dó tì í, kí o sì mọ ilé ìṣọ́ tì í, kí o sì mọ odi tì í, kí o sì gbé ogun sí i, kí o sì to òòlù yí i ká.

3. Kí o sì fi páànù irin kan ṣe ògiri láàrin rẹ̀ àti ìlú yìí, dojú kọ ọ́, kí o sì gbógun tì í. Èyí yóò jẹ́ àmì fún ilé Ísírẹ́lì.

4. “Lẹ́yìn èyí, lọ fi ẹ̀gbẹ́ òsì dúbúlẹ̀, kí o sì gbé ẹ̀ṣẹ̀ ilé Ísírẹ́lì lé orí ara rẹ. Iye ọjọ́ tí ìwọ bá fi sùn náà ni ìwọ yóò fi ru ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

Ísíkẹ́lì 4