Ámósì 8:11-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. “Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa Ọlọ́run wí,“nígbà tí èmi yóò rán ìyàn sí ilẹ̀ náà,kì í ṣe ìyàn oúnjẹ tàbí òùngbẹ fún omi.Ṣùgbọ́n ìyàn gbígbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.

12. Àwọn ènìyàn yóò rìn kiri láti òkun dé òkunwọn yóò sì máa rìn ká láti gúṣù sí àríwá,wọn yóò máa wá ọ̀rọ̀ Olúwaṣùgbọ́n wọn kì yóò rí i.

13. “Ní ọjọ́ náà“àwọn arẹwà wúndíá àti àwọn alágbára ọ̀dọ́mọkùnrinyóò dákú fún òùngbẹ omi.

14. Àwọn tí ó fi òrìṣà Samaríà búra tí wọ́n wí pé,‘tí wọ́n sì wí pé, ìwọ Dánì, ọlọ́run rẹ ń bẹ láàyè,’àti bi ó ti dájú pé ọlọ́run Báṣébà ti ń bẹ láàyèàní, wọn yóò ṣubú, wọn kì yóò sì tún dìde mọ́.’ láàyè ìwọ Dánì.’Bí ó ti dájú pè ọlọrun rẹ ń bẹ láàyè ìwọ BáṣébàWọ́n yóò ṣubú,Wọn kì yóò si tún díde mọ.”

Ámósì 8