Ámósì 4:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ẹ̀yin màlúù Báṣánì lórí òkè Samáríà,ẹ̀yin obìnrin tí ó ń ni talákà lára,tí ó ń tẹ aláìní mọ́lẹ̀, tí ó wí fún ọkọ rẹ̀, “Gbé wá kí a sì mu!”

2. Olúwa Ọlọ́run ti fi ìwà mímọ́ rẹ̀ búra:“Àkókò náà yóò dé nítòótọ́nígbà tí a ó fi ìwọ̀ mú un yín lọ,ẹni tí ó kẹ́yìn pẹ̀lú ìwọ̀ ẹja.

3. Ẹni kọ̀ọ̀kan yín yóò jáde lọgba àárin odi yíyaa ó sì lé e yín sí Hámónà,”ni Olúwa wí.

4. “Ẹ lọ sí Bétélì láti dẹ́ṣẹ̀;ẹ lọ sí Gílígálì kí ẹ sì dẹ́ṣẹ̀ sí i.Ẹ mú ẹbọ sísun yín láràárọ̀ wá,ìdámẹ́wàá yín ní ọdọdún mẹ́ta.

5. Kí ẹ mú ọrẹ́ ìdúpẹ́ ìyẹ̀fun tí a sunkí ẹ sì mú ọrẹ àtinúwálọ fi wọ́n yagàn, ẹ̀yin ènìyàn Ísírẹ́lì,nítorí èyí ni ẹ fẹ́ láti ṣe,”ni Olúwa Ọlọ́run wí.

6. “Èmi fún un yín ní inú òfìfo ní gbogbo ìlúàti láìní àkàrà ní gbogbo ibùgbé yín,ṣíbẹ̀, ẹ̀yin kò tí ì yípadà sími,”ni Olúwa wí.

Ámósì 4