24. Ṣùgbọ́n ẹ̀yìn ko já sí nǹkankaniṣẹ́ yín ni kò sì wúlò fún ohunkóhun;ẹni tí ó yàn yín jẹ́ ẹni ìríra.
25. “Èmi ti ru ẹnìkan sókè láti àríwá, òun sì ń bọẹnìkan láti ìlà oòrùn tí ó pe orúkọ mi.Òun gun àwọn aláṣẹ mọ́lẹ̀ bí ẹni pé odò ni wọ́n,àfi bí ẹni pé amọ̀kòkò nì ti ń gún amọ̀.
26. Ta ni ó sọ èyí láti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀,tí àwa kò bá fi mọ̀,tàbí ṣáájú àkókò, tí àwa kò bá fi wí pé,‘Òun sọ òtítọ́’?Ẹnikẹ́ni kò sọ nípa èyí,ẹnikẹ́ni kò sàṣọtẹ́lẹ̀ rẹ̀,ẹnikẹ́ni kò gbọ́ ọ̀rọ̀ kan láti ọ̀dọ̀ rẹ̀.
27. Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ tí ó sọ fún Ṣíhóńì pé,‘Wò ó, àwọn nìyìí!’Mo fún Jérúsálẹ́mù ní ìránṣẹ́ ìhìn ayọ̀ kan.
28. Èmi wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan—kò sí ẹnìkan nínú wọn tí ó lè mú ìmọ̀ràn wá,kò sí ẹnìkan tí ó lè dáhùn nígbà tí mo bi wọ́n.
29. Kíyèsí i, irọ́ ni gbogbo wọn!Gbogbo ìṣe wọn já sí asán;àwọn ère wọn kò ṣé kò yà fúnafẹ́fẹ́ àti dàrúdàpọ̀.