1 Kọ́ríńtì 11:30-34 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

30. Ìdí nìyìí tí ọ̀pọ̀ yín fi di ẹni tí kò lágbára mọ́, tí ọ̀pọ̀ yín sì ń sàìsàn, àwọn mìíràn nínú yín tilẹ̀ ti sùn.

31. Ṣùgbọ́n tí ẹ bá yẹ ara yín wò dáadáa, kí ẹ tó jẹ ẹ́, a kì yóò dá yín lẹ́jọ́.

32. Ṣíbẹ̀ṣíbẹ̀ ti Olúwa bá tilẹ̀ ṣe ìdájọ́ wa, tí ó sì jẹ wá níyà nítorí àwọn àṣìṣe wa, ó dára bẹ́ẹ̀, ó ń ṣe bẹ́ẹ̀, kí a má baà dá wa lẹ́jọ́, kí a sì pa wá run pẹ̀lú ayé.

33. Nítorí náà, ẹ̀yin arákùnrin mi ọ̀wọ́n, nígbàkúùgbà ti ẹ bá péjọ láti jẹ́ oúnjẹ alẹ́ Olúwa, tàbi fún ìsìn oúnjẹ alẹ́ Olúwa, ẹ dúró de ara yín.

34. Bí ebi bá ń pa ẹnikẹ́ni nínú yin, kí ó jẹun láti ilé wá, kí ó má baá mú ìjìyà wá sórí ara rẹ̀ nígbà tí ẹ bá pé jọ.Tí mo bá dé, èmi yóò máa sọ̀rọ̀ lórí àwọn kókó ọ̀rọ̀ ìyókù tí n kò ì ti fẹnu bà lẹ́sẹsẹ.

1 Kọ́ríńtì 11