Owe 5:1-7 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. ỌMỌ mi, fiyesi ọgbọ́n mi, ki o si dẹti rẹ si oye mi.

2. Lati ma pa ironu mọ́, ati ki ète rẹ ki o le ma pa ìmọ mọ́.

3. Nitori ti ète awọn ajeji obinrin a ma kán bi oyin, ẹnu rẹ̀ si kunna ju ororo lọ:

4. Ṣugbọn igbẹhin rẹ̀ koro bi idápa, o si mú bi idà olojumeji.

5. Ẹsẹ rẹ̀ nsọkalẹ lọ sinu ikú, ìrin-ẹsẹ rẹ̀ de ipo-okú.

6. Ki iwọ má ba ja ipa-ọ̀na ìye, ipa-ọ̀na rẹ̀ a ma yi sihin yi sọhun, on kò si mọ̀.

7. Njẹ gbọ́ temi nisisiyi, ẹnyin ọmọ, ki ẹnyin ki o máṣe yà kuro li ọ̀rọ ẹnu mi.

Owe 5