O. Daf 89:15-18 Yorùbá Bibeli (YCE)

15. Ibukún ni fun awọn enia ti o mọ̀ ohùn ayọ̀ nì: Oluwa, nwọn o ma rìn ni imọlẹ oju rẹ.

16. Li orukọ rẹ ni nwọn o ma yọ̀ li ọjọ gbogbo: ati ninu ododo rẹ li a o ma gbé wọn leke.

17. Nitori iwọ li ogo agbara wọn: ati ninu ore ojurere rẹ li a o gbé iwo wa soke,

18. Nitori Oluwa li asà wa: Ẹni-Mimọ́ Israeli li ọba wa.

O. Daf 89