O. Daf 88:1-5 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. OLUWA Ọlọrun igbala mi, emi nkigbe lọsan ati loru niwaju rẹ.

2. Jẹ ki adura mi ki o wá si iwaju rẹ: dẹ eti rẹ silẹ si igbe mi.

3. Nitori ti ọkàn mi kún fun ipọnju, ẹmi mi si sunmọ isa-okú.

4. A kà mi pẹlu kún awọn ti o sọkalẹ lọ si ihò: emi dabi ọkunrin ti kò ni ipá.

5. Ẹniti a kọ̀ silẹ lãrin awọn okú, bi awọn ẹni pipa ti o dubulẹ ni isa-okú, ẹniti iwọ kò ranti mọ́: a si ke wọn kuro nipa ọwọ rẹ.

O. Daf 88