O. Daf 78:21-25 Yorùbá Bibeli (YCE)

21. Nitorina, Oluwa gbọ́ eyi, o binu: bẹ̃ni iná ràn ni Jakobu, ibinu si ru ni Israeli;

22. Nitori ti nwọn kò gbà Ọlọrun gbọ́, nwọn kò si gbẹkẹle igbala rẹ̀.

23. O paṣẹ fun awọsanma lati òke wá, o si ṣi ilẹkùn ọrun silẹ.

24. O si rọ̀jo Manna silẹ fun wọn ni jijẹ, o si fun wọn li ọkà ọrun.

25. Enia jẹ onjẹ awọn angeli; o rán onjẹ si wọn li ajẹyo.

O. Daf 78