O. Daf 76:1-6 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. NI Juda li a gbe mọ̀ Ọlọrun: orukọ rẹ̀ si pọ̀ ni Israeli.

2. Ni Salemu pẹlu li agọ rẹ̀ wà, ati ibujoko rẹ̀ ni Sioni.

3. Nibẹ li o gbe ṣẹ́ ọfà, ọrun, apata, ati idà, ati ogun na.

4. Iwọ li ogo ati ọlá jù òke-nla ikogun wọnni lọ.

5. A kó awọn alaiya lile ni ikogun, nwọn ti sùn orun wọn, gbogbo ọkunrin alagbara kò si ri ọwọ wọn.

6. Nipa ibawi rẹ, Ọlọrun Jakobu, ati kẹkẹ́-ogun ati ẹṣin sun orun asunkú.

O. Daf 76