O. Daf 73:14-17 Yorùbá Bibeli (YCE)

14. Nitoripe ni gbogbo ọjọ li a nyọ mi lẹnu, a si nnà mi li orowurọ.

15. Bi emi ba pe, emi o fọ̀ bayi: kiyesi i, emi o ṣẹ̀ si iran awọn ọmọ rẹ.

16. Nigbati mo rò lati mọ̀ eyi, o ṣoro li oju mi.

17. Titi mo fi lọ sinu ibi-mimọ́ Ọlọrun; nigbana ni mo mọ̀ igbẹhin wọn.

O. Daf 73