O. Daf 60:6-11 Yorùbá Bibeli (YCE)

6. Ọlọrun ti sọ̀rọ ninu ìwa-mimọ́ rẹ̀ pe; Emi o yọ̀, emi o pin Ṣekemu, emi o si wọ̀n afonifoji Sukkotu.

7. Ti emi ni Gileadi, ti emi ni Manasse; Efraimu pẹlu li agbara ori mi; Juda li olofin mi;

8. Moabu li ikoko-iwẹsẹ mi; lori Edomu li emi o bọ́ bàta mi si: Filistia ma ho iho ayọ̀ fun mi!

9. Tani yio mu mi wá sinu ilu olodi nì? tani yio sin mi lọ si Edomu?

10. Iwọ ha kọ́, Ọlọrun, ẹniti o ṣa wa tì? ati iwọ, Ọlọrun, ti kò ba ogun wa jade lọ?

11. Fun wa ni iranlọwọ ninu ipọnju: nitori pe asan ni iranlọwọ enia.

O. Daf 60