O. Daf 6:5-9 Yorùbá Bibeli (YCE)

5. Nitoriti kò si iranti rẹ ninu okú: ninu isa okú tani yio dupẹ fun ọ?

6. Agara ikerora mi da mi: li oru gbogbo li emi nmu ẹní mi fó li oju omi; emi fi omije mi rin ibusùn mi.

7. Oju mi bajẹ tan nitori ibinujẹ; o di ogbó tan nitori gbogbo awọn ọta mi.

8. Ẹ lọ kuro lọdọ mi, gbogbo ẹnyin oniṣẹ ẹ̀ṣẹ; nitori ti Oluwa gbọ́ ohùn ẹkún mi.

9. Oluwa gbọ́ ẹ̀bẹ mi; Oluwa yio gbà adura mi.

O. Daf 6