O. Daf 37:28-33 Yorùbá Bibeli (YCE)

28. Nitoriti Oluwa fẹ idajọ, kò si kọ̀ awọn enia mimọ́ rẹ̀ silẹ; a si pa wọn mọ́ lailai: ṣugbọn iru-ọmọ awọn enia buburu li a o ke kuro.

29. Olododo ni yio jogun aiye, yio si ma gbe inu rẹ̀ lailai.

30. Ẹnu olododo ni ima sọ̀rọ ọgbọ́n, ahọn rẹ̀ a si ma sọ̀rọ idajọ.

31. Ofin Ọlọrun rẹ̀ mbẹ li aiya rẹ̀; ọkan ninu ìrin rẹ̀ kì yio yẹ̀.

32. Ẹni buburu nṣọ olododo, o si nwá ọ̀na lati pa a.

33. Oluwa kì yio fi i le e lọwọ, kì yio si da a lẹbi, nigbati a ba nṣe idajọ rẹ̀.

O. Daf 37