O. Daf 37:15-21 Yorùbá Bibeli (YCE)

15. Idà wọn yio wọ̀ aiya wọn lọ, ọrun wọn yio si ṣẹ́.

16. Ohun diẹ ti olododo ni sanju ọrọ̀ ọ̀pọ enia buburu.

17. Nitoriti a o ṣẹ́ apa awọn enia buburu: ṣugbọn Oluwa di olododo mu.

18. Oluwa mọ̀ ọjọ ẹni iduro-ṣinṣin: ati ilẹ-ini wọn yio wà lailai.

19. Oju kì yio tì wọn ni igba ibi: ati li ọjọ ìyan a o tẹ́ wọn lọrun.

20. Ṣugbọn awọn enia buburu yio ṣegbe, awọn ọta Oluwa yio dabi ẹwà oko-tutu: nwọn o run; ẹ̃fin ni nwọn o run si.

21. Awọn enia buburu wín, nwọn kò si pada san: ṣugbọn olododo a ma ṣãnu, a si ma fi funni.

O. Daf 37