O. Daf 144:2-8 Yorùbá Bibeli (YCE)

2. Õre mi, ati odi-agbara mi; ile-iṣọ giga, ati olugbala mi; asà mi, ati ẹniti mo gbẹkẹle; eniti o tẹri awọn enia mi ba labẹ mi.

3. Oluwa, kili enia, ti iwọ fi nkiye si i! tabi ọmọ enia, ti iwọ fi nronú rẹ̀!

4. Enia dabi asan: bi ojìji ti nkọja lọ li ọjọ rẹ̀.

5. Oluwa, tẹ̀ ọrun rẹ ba, ki o si sọ̀kalẹ: tọ́ awọn òke nla, nwọn o si ru ẽfin.

6. Kọ manamana jade, ki o si tú wọn ka: ta ọfà rẹ ki o si dà wọn rú.

7. Rán ọwọ rẹ lati òke wá; yọ mi, ki o si gbà mi kuro ninu omi nla, li ọwọ awọn ọmọ àjeji.

8. Ẹnu ẹniti nsọ̀rọ asan, ọwọ ọtún wọn si jẹ ọwọ ọtún eke.

O. Daf 144