O. Daf 119:29-42 Yorùbá Bibeli (YCE)

29. Mu ọ̀na eke kuro lọdọ mi: ki o si fi ore-ọfẹ fi ofin rẹ fun mi.

30. Emi ti yàn ọ̀na otitọ: idajọ rẹ ni mo fi lelẹ niwaju mi.

31. Emi ti faramọ ẹri rẹ: Oluwa, máṣe dojutì mi.

32. Emi o ma sare li ọ̀na aṣẹ rẹ, nitori iwọ bùn aiya mi laye.

33. Oluwa, kọ́ mi li ọ̀na rẹ; emi o si ma pa a mọ́ de opin.

34. Fun mi li oye, emi o si pa ofin rẹ mọ́; nitõtọ, emi o ma kiyesi i tinutinu mi gbogbo.

35. Mu mi rìn ni ipa aṣẹ rẹ; nitori ninu rẹ̀ ni didùn inu mi.

36. Fa aiya mi si ẹri rẹ, ki o má si ṣe si oju-kòkoro.

37. Yi oju mi pada kuro lati ma wò ohun asan; mu mi yè li ọna rẹ.

38. Fi ọ̀rọ rẹ mulẹ si iranṣẹ rẹ, ti iṣe ti ìbẹru rẹ̀.

39. Yi ẹ̀gan mi pada ti mo bẹ̀ru: nitori ti idajọ rẹ dara.

40. Kiyesi i, ọkàn mi ti fà si ẹkọ́ rẹ: sọ mi di ãye ninu ododo rẹ.

41. Jẹ ki ãnu rẹ ki o tọ̀ mi wá pẹlu, Oluwa, ani igbala rẹ gẹgẹ bi ọ̀rọ rẹ.

42. Bẹ̃li emi o ni ọ̀rọ ti emi o fi da ẹni ti ngàn mi lohùn; nitori mo gbẹkẹle ọ̀rọ rẹ.

O. Daf 119