O. Daf 116:16-19 Yorùbá Bibeli (YCE)

16. Oluwa nitõtọ iranṣẹ rẹ li emi; iranṣẹ rẹ̀ li emi, ati ọmọ iranṣẹ-birin rẹ: iwọ ti tú ìde mi.

17. Emi o ru ẹbọ ọpẹ si ọ, emi o ma ke pè orukọ Oluwa.

18. Emi o san ileri ifẹ mi fun Oluwa, nitõtọ li oju gbogbo awọn enia rẹ̀.

19. Ninu àgbala ile Oluwa, li arin rẹ, iwọ Jerusalemu. Ẹ yìn Oluwa.

O. Daf 116