O. Daf 102:18-22 Yorùbá Bibeli (YCE)

18. Eyi li a o kọ fun iran ti mbọ̀; ati awọn enia ti a o da yio ma yìn Oluwa.

19. Nitori ti o wò ilẹ lati òke ibi-mimọ́ rẹ̀ wá; lati ọrun wá ni Oluwa bojuwo aiye;

20. Lati gbọ́ irora ara-tubu; lati tú awọn ti a yàn si ikú silẹ;

21. Lati sọ orukọ Oluwa ni Sioni, ati iyìn rẹ̀ ni Jerusalemu.

22. Nigbati a kó awọn enia jọ pọ̀ ati awọn ijọba, lati ma sìn Oluwa.

O. Daf 102