O. Daf 102:1-7 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. GBỌ adura mi, Oluwa, ki o si jẹ ki igbe mi ki o wá sọdọ rẹ.

2. Máṣe pa oju rẹ mọ́ kuro lara mi li ọjọ ti emi wà ninu ipọnju; dẹ eti rẹ si mi: li ọjọ ti mo ba pè, da mi lohùn-lọgan.

3. Nitori ti ọjọ mi run bi ẹ̃fin, egungun mi si jona bi àro.

4. Aiya mi lù, o si rọ bi koriko; tobẹ̃ ti mo gbagbe lati jẹ onjẹ mi.

5. Nitori ohùn ikerora mi, egungun mi lẹ̀ mọ ẹran-ara mi.

6. Emi dabi ẹiyẹ ofú ni iju: emi dabi owiwi ibi ahoro.

7. Emi nṣọra, emi dabi ologoṣẹ nikan ni ori ile.

O. Daf 102