Neh 7:5-12 Yorùbá Bibeli (YCE)

5. Ọlọrun mi si fi si mi li ọkàn lati ko awọn ijòye jọ, ati awọn olori, ati awọn enia, ki a le kà wọn nipa idile wọn. Mo si ri iwe idile awọn ti o kọ́ goke wá, mo ri pe, a kọ ọ sinu rẹ̀.

6. Wọnyi ni awọn ọmọ igberiko, ti o gòke wá lati ìgbekun ninu awọn ti a ti ko lọ, ti Nebukadnesari ọba Babiloni ti ko lọ, ti nwọn tun padà wá si Jerusalemu, ati si Juda, olukuluku si ilu rẹ̀.

7. Awọn ti o ba Serubbabeli wá, Jeṣua, Nehemia, Asariah, Raamiah, Nahamani, Mordikai, Bilṣani, Mispereti, Bigfai, Nehumu, Baana. Iye awọn ọkunrin enia Israeli li eyi;

8. Awọn ọmọ Paroṣi, ẹgbã o le mejilelãdọsan.

9. Awọn ọmọ Ṣefatiah, ojidinirinwo o le mejila.

10. Awọn ọmọ Ara, adọtalelẹgbẹta o le meji.

11. Awọn ọmọ Pahat-moabu, ti awọn ọmọ Jeṣua, ati Joabu, ẹgbẹrinla o le mejidilogun.

12. Awọn ọmọ Elamu, ẹgbẹfa o le mẹrinlelãdọta.

Neh 7