Neh 11:5-16 Yorùbá Bibeli (YCE)

5. Ati Maaseiah ọmọ Baruku, ọmọ Kol-hose, ọmọ Hasaiah, ọmọ Adaiah, ọmọ Joiaribu, ọmọ Sekariah, ọmọ Ṣiloni.

6. Gbogbo ọmọ Peresi ti ngbe Jerusalemu jẹ adọrinlenirinwo o di meji, alagbara ọkunrin.

7. Wọnyi li awọn ọmọ Benjamini; Sallu ọmọ Meṣullamu ọmọ Joedi, ọmọ Pedaiah, ọmọ Kolaiah, ọmọ Maaseiah, ọmọ Itieli, ọmọ Jesaiah.

8. Ati lẹhin rẹ̀ Gabbai, Sallai, ọrindilẹgbẹrun o le mẹjọ.

9. Joeli ọmọ Sikri si ni alabojuto wọn; ati Juda ọmọ Senua ni igbakeji ni ilu.

10. Ninu awọn alufa: Jedaiah ọmọ Joiaribu, Jakini.

11. Seraiah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitibu, ni olori ile Ọlọrun.

12. Awọn arakunrin wọn ti o ṣe iṣẹ ile na jẹ, ẹgbẹrin o le mejilelogun: ati Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Pelaliah, ọmọ Amsi, ọmọ Sekariah, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah,

13. Ati awọn arakunrin rẹ̀, awọn olori awọn baba, ojilugba o le meji: ati Amaṣai ọmọ Asareeli, ọmọ Ahasai, ọmọ Meṣillemoti, ọmọ Immeri,

14. Ati awọn arakunrin wọn, alagbara li ogun, mejidilãdoje: ati olori wọn ni Sabdieli ọmọ ọkan ninu awọn enia nla.

15. Ninu awọn ọmọ Lefi pẹlu: Ṣemaiah, ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah, ọmọ Bunni;

16. Ati Ṣabbetai ati Josabadi, ninu olori awọn ọmọ Lefi ni alabojuto iṣẹ ode ile Ọlọrun.

Neh 11