Neh 11:17-22 Yorùbá Bibeli (YCE)

17. Ati Mattaniah ọmọ Mika, ọmọ Sabdi, ọmọ Asafu, ni olori lati bẹ̀rẹ idupẹ ninu adura: ati Bakbukiah ẹnikeji ninu awọn arakunrin rẹ̀, ati Abda ọmọ Ṣammua, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni.

18. Gbogbo awọn ọmọ Lefi ninu ilu mimọ́ jẹ ọrinlugba o le mẹrin.

19. Ati awọn adèna, Akkubu, Talmoni, ati awọn arakunrin wọn ti nṣọ ẹnu ọ̀na jẹ mejilelãdọsan.

20. Ati iyokù Israeli, ti awọn alufa, ati ti awọn ọmọ Lefi, wà ni gbogbo ilu Juda, olukuluku ninu ilẹ ìni rẹ̀.

21. Ṣugbọn awọn Netinimu ngbe Ofeli: ati Siha, ati Gispa wà li olori awọn Netinimu.

22. Ati alabojuto awọn ọmọ Lefi ni Jerusalemu ni Ussi ọmọ Bani, ọmọ Haṣabiah, ọmọ Mattaniah, ọmọ Mika. Ninu awọn ọmọ Asafu, awọn akọrin wà lori iṣẹ ile Ọlọrun.

Neh 11