Luk 2:26-34 Yorùbá Bibeli (YCE)

26. A si ti fihàn a lati ọdọ Ẹmí Mimọ́ na wá pe, on kì yio ri ikú, ki o to ri Kristi Oluwa.

27. O si ti ipa Ẹmí wá sinu tẹmpili: nigbati awọn obi rẹ̀ si gbé ọmọ na Jesu wá, lati ṣe fun u bi iṣe ofin.

28. Nigbana li o gbé e li apa rẹ̀, o fi ibukun fun Ọlọrun, o ni,

29. Oluwa, nigbayi li o to jọwọ ọmọ-ọdọ rẹ lọwọ lọ li alafia, gẹgẹ bi ọ̀rọ rẹ:

30. Nitoriti oju mi ti ri igbala rẹ na,

31. Ti iwọ ti pèse silẹ niwaju enia gbogbo;

32. Imọlẹ lati mọ́ si awọn Keferi, ati ogo Israeli enia rẹ.

33. Ẹnu si yà Josefu ati iya rẹ̀ si nkan ti a nsọ si i wọnyi.

34. Simeoni si sure fun wọn, o si wi fun Maria iya rẹ̀ pe, Kiyesi i, a gbé ọmọ yi kalẹ fun iṣubu ati idide ọ̀pọ enia ni Israeli; ati fun àmi ti a nsọ̀rọ òdi si;

Luk 2