Joh 1:5-11 Yorùbá Bibeli (YCE)

5. Imọlẹ na si nmọlẹ ninu òkunkun; òkunkun na kò si bori rẹ̀.

6. Ọkunrin kan wà ti a rán lati ọdọ Ọlọrun wá, orukọ ẹniti njẹ Johanu.

7. On na li a si rán fun ẹri, ki o le ṣe ẹlẹri fun imọlẹ na, ki gbogbo enia ki o le gbagbọ́ nipasẹ rẹ̀.

8. On kì iṣe imọlẹ̀ na, ṣugbọn a rán a wá lati ṣe ẹlẹri fun Imọlẹ na.

9. Imọlẹ otitọ mbẹ ti ntàn mọlẹ fun olúkulùku enia ti o wá si aiye.

10. On si wà li aiye, nipasẹ rẹ̀ li a si ti da aiye, aiye kò si mọ̀ ọ.

11. O tọ̀ awọn tirẹ̀ wá, awọn ará tirẹ̀ kò si gbà a.

Joh 1