Job 9:4-24 Yorùbá Bibeli (YCE)

4. Ọlọgbọ́n-ninu ati alagbara ni ipá li on; tali o ṣagidi si i, ti o si gbè fun u ri?

5. Ẹniti o ṣi okè ni idi, ti nwọn kò si mọ̀: ti o tari wọn ṣubu ni ibinu rẹ̀.

6. Ti o mì ilẹ aiye tìti kuro ni ipò rẹ̀, ọwọ̀n rẹ̀ si mì tìti.

7. Ti o paṣẹ fun õrùn, ti on kò si là, ti o si dí irawọ̀ mọ́.

8. On nikanṣoṣo li o na oju ọrun lọ, ti o si nrìn lori ìgbì okun.

9. Ẹniti o da irawọ̀ Arketuru, Orioni ati Pleiade ati iyàra pipọ ti gusu.

10. Ẹniti nṣe ohun ti o tobi jù awari lọ, ani ohun iyanu laini iye.

11. Kiyesi i, on kọja lọ li ẹ̀ba ọdọ mi, emi kò si ri i, o si kọja siwaju, bẹ̃li emi kò ri oju rẹ̀.

12. Kiyesi i, o jãgbà lọ, tani yio fa a pada? tani yio bi i pe, kini iwọ nṣe nì?

13. Ọlọrun kò ni fà ibinu rẹ̀ sẹhin, awọn oniranlọwọ ìgberaga a si tẹriba labẹ rẹ̀.

14. Ambọtori emi ti emi o fi dá a lohùn, ti emi o fi má ṣa ọ̀rọ awawì mi ba a ṣawiye?

15. Bi o tilẹ ṣepe mo ṣe olododo, emi kò gbọdọ̀ da a lohùn, ṣugbọn emi o gbadura ẹ̀bẹ mi sọdọ onidajọ mi.

16. Bi emi ba si kepè e, ti on si da mi lohùn, emi kì yio si gbagbọ pe, on ti feti si ohùn mi.

17. Nitoripe o fi ẹ̀fufu nla ṣẹ mi tutu, o sọ ọgbẹ mi di pipọ lainidi.

18. On kì yio jẹ ki emi ki o fà ẹmi mi, ṣugbọn o fi ohun kikorò kún u fun mi.

19. Bi mo ba sọ ti agbara, wò o! alagbara ni, tabi niti idajọ, tani yio da akoko fun mi lati rò?

20. Bi mo tilẹ da ara mi lare, ẹnu ara mi ni yio dá mi lẹbi; bi mo wipe, olododo li emi, yio si fi mi hàn ni ẹni-òdi.

21. Olõtọ ni mo ṣe, sibẹ emi kò kiyesi ẹmi mi, ìwa mi li emi iba ma gàn.

22. Ohun kanna ni, nitorina ni emi ṣe sọ ọ: on a pa ẹni-otitọ ati enia buburu pẹlu.

23. Bi jamba ba pa ni lojijì, yio rẹrin idanwo alaiṣẹ̀.

24. A fi aiye le ọwọ enia buburu; o si bò awọn onidajọ rẹ̀ li oju; bi kò ba ri bẹ̃, njẹ tani?

Job 9