Job 21:2-11 Yorùbá Bibeli (YCE)

2. Ẹ tẹti silẹ dẹdẹ si ohùn mi, ki eyi ki o jasi itunu nyin.

3. Ẹ jọwọ mi ki emi sọ̀rọ, lẹhin igbati mo ba sọ tan, iwọ ma fi ṣẹsin nṣo.

4. Bi o ṣe ti emi ni, aroye mi iṣe si enia bi, tabi ẽtiṣe ti ọkàn mi kì yio fi ṣe aibalẹ?

5. Ẹ wò mi fin, ki ẹnu ki o si yà nyin, ki ẹ si fi ọwọ le ẹnu nyin.

6. Ani nigbati mo ranti, ẹ̀ru bà mi, iwarìri si mu mi lara.

7. Nitori kini enia buburu fi wà li ãyè, ti nwọn gbọ́, ani ti nwọn di alagbara ni ipa!

8. Iru-ọmọ wọn fi idi kalẹ li oju wọn pẹlu wọn, ati ọmọ-ọmọ wọn li oju wọn.

9. Ile wọn wà laini ewu, bẹ̃ni ọpa-ìna Ọlọrun kò si lara wọn.

10. Akọ-malu wọn a ma gùn, kì isi isé, abomalu wọn a ma bi, ki isi iṣẹnu;

11. Nwọn a ma rán awọn ọmọ wọn wẹwẹ jade bi agbo ẹran, awọn ọmọ wọn a si ma jó.

Job 21