Jer 50:17-24 Yorùbá Bibeli (YCE)

17. Israeli jẹ́ agutan ti o ṣina kiri, awọn kiniun ti le e lọ: niṣaju ọba Assiria pa a jẹ, ati nikẹhin yi Nebukadnessari, ọba Babeli, sán egungun rẹ̀.

18. Nitorina bayi li Oluwa awọn ọmọ-ogun, Ọlọrun Israeli wi pe, wò o, emi o jẹ ọba Babeli ati ilẹ rẹ̀ niya, gẹgẹ bi emi ti jẹ ọba Assiria niya.

19. Emi o si tun mu Israeli wá si ibugbe rẹ̀, on o si ma bọ ara rẹ̀ lori Karmeli, ati Baṣani, a o si tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọrun li oke Efraimu ati ni Gileadi.

20. Li ọjọ wọnni, ati li akoko na, li Oluwa wi, a o wá aiṣedẽde Israeli kiri, ṣugbọn kì o si mọ́; ati ẹ̀ṣẹ Juda, a kì o si ri wọn: nitori emi o dariji awọn ti mo mu ṣẹkù.

21. Goke lọ si ilẹ ọlọtẹ li ọ̀na meji, ani sori rẹ̀ ati si awọn olugbe ilu Ibẹwo: sọ ọ di ahoro ki o si parun lẹhin wọn, li Oluwa wi, ki o si ṣe gẹgẹ bi gbogbo eyiti emi ti paṣẹ fun ọ.

22. Iró ogun ni ilẹ na, ati ti iparun nla!

23. Bawo li a ti fọ, ti a si ṣẹ olú gbogbo ilẹ aiye! Bawo ni Babeli di ahoro lãrin awọn orilẹ-ède!

24. Emi ti kẹ okùn fun ọ, a si mu ọ, iwọ Babeli, iwọ kò si mọ̀: a ri ọ, a si mu ọ pẹlu, nitoripe iwọ ti ba Oluwa ja.

Jer 50