Jer 20:11-17 Yorùbá Bibeli (YCE)

11. Ṣugbọn Oluwa mbẹ lọdọ mi bi akọni ẹlẹrù, nitorina awọn ti nṣe inunibini si mi yio ṣubu, nwọn kì yio le bori: oju yio tì wọn gidigidi, nitoripe nwọn kì o ṣe rere: a ki yio gbagbe itiju wọn lailai!

12. Oluwa awọn ọmọ-ogun, iwọ ti ndán olododo wò, iwọ si ri inu ati ọkàn, emi o ri ẹsan rẹ lara wọn: nitoriti mo ti fi ọ̀ran mi le ọ lọwọ!

13. Ẹ kọrin si Oluwa, ẹ yìn Oluwa, nitoriti o ti gbà ọkàn talaka kuro lọwọ awọn oluṣe buburu.

14. Egbe ni fun ọjọ na ti a bi mi! ọjọ na ti iya mi bi mi, ki o má ri ibukun!

15. Egbe ni fun ọkunrin na ti o mu ihìn tọ̀ baba mi wá, wipe, Ọmọkunrin li a bi fun ọ; o mu u yọ̀.

16. Ki ọkunrin na ki o si dabi ilu wọnni ti Oluwa ti bì ṣubu, li aiyi ọkàn pada, ki o si gbọ́ ẹkun li owurọ, ati ọ̀fọ li ọsangangan.

17. Nitoriti kò pa mi ni inu iya mi, tobẹ̃ ki iya mi di isà mi, ki o loyun mi lailai.

Jer 20