2. Kro 9:29-31 Yorùbá Bibeli (YCE)

29. Ati iyokù iṣe Solomoni ti iṣaju ati ti ikẹhin, a kọ ha kọ wọn sinu iwe Natani woli, ati sinu asọtẹlẹ Ahijah, ara Ṣilo, ati sinu iran Iddo, ariran, sipa Jeroboamu, ọmọ Nebati.

30. Solomoni si jọba ni Jerusalemu lori gbogbo Israeli li ogoji ọdun.

31. Solomoni si sùn pẹlu awọn baba rẹ̀, a si sìn i ni ilu Dafidi baba rẹ̀: Rehoboamu, ọmọ rẹ̀ si jọba ni ipò rẹ̀.

2. Kro 9