2. Kro 26:2-6 Yorùbá Bibeli (YCE)

2. On kọ́ Elotu, o si mu u pada fun Juda; lẹhin ti ọba sùn pẹlu awọn baba rẹ̀.

3. Ẹni ọdun mẹrindilogun ni Ussiah, nigbati o bẹ̀rẹ si ijọba, o si jọba ọdun mejilelãdọta ni Jerusalemu. Orukọ iya rẹ̀ si ni Jekoliah ti Jerusalemu.

4. O si ṣe eyiti o tọ́ li oju Oluwa, gẹgẹ bi gbogbo eyiti baba rẹ̀, Amasiah, ti ṣe.

5. O si wá Ọlọrun li ọjọ Sekariah, ẹniti o li oye ninu iran Ọlọrun: niwọn ọjọ ti o wá Oluwa, Ọlọrun si mu u ṣe rere.

6. O si jade lọ, o si ba awọn ara Filistia jagun, o si wó odi Gati ati odi Jabne ati odi Aṣdodu, o si kọ́ ilu wọnni ni Aṣdodu, ati lãrin awọn ara Filistia.

2. Kro 26