2. Kro 26:13-18 Yorùbá Bibeli (YCE)

13. Ati li ọwọ wọn li agbara ogun kan wà, ọkẹ mẹdogun enia o le ẹ̃dẹgbãrin ti o mura, ti nfi àgbara nla jagun, lati ràn ọba lọwọ si ọta.

14. Ussiah si pesè fun wọn, já gbogbo ogun na, asà ati ọ̀kọ, ati akoro, ati ohun ihamọra-ọrùn, ati ọrun titi de okuta kànakàna.

15. O si ṣe ohun ẹrọ-ijagun ni Jerusalemu, ihumọ ọlọgbọ́n enia, lati wà lori ile-iṣọ, ati lori igun odi, lati fi tafa, ati lati fi sọ okuta nla. Orukọ rẹ̀ si tàn lọ jìnajina, nitoriti a ṣe iranlọwọ iyanu fun u, titi o fi li agbara.

16. Ṣugbọn nigbati o li agbara tan, ọkàn rẹ̀ gbé ga soke si iparun; nitoriti o ṣe irekọja si Oluwa Ọlọrun rẹ̀, o si lọ sinu tempili Oluwa, lati sun turari lori pẹpẹ turari.

17. Asariah, alufa si wọle tọ̀ ọ lọ ati ọgọrin alufa Oluwa pẹlu rẹ̀, awọn alagbara,

18. Nwọn si tako Ussiah ọba, nwọn si wi fun u pe, Ki iṣe tirẹ, Ussiah, lati sun turari fun Oluwa, bikòṣe ti awọn alufa, awọn ọmọ Aaroni ti a yà si mimọ́ lati sun turari: jade kuro ni ibi mimọ́; nitoriti iwọ ti dẹṣẹ; bẹ̃ni kì yio ṣe fun ọlá rẹ lati ọdọ Oluwa Ọlọrun.

2. Kro 26