1. NIGBANA ni gbogbo enia Juda mu Ussiah ti iṣe ẹni ọdun mẹrindilogun, nwọn si fi i jọba ni ipò baba rẹ̀, Amasiah.
2. On kọ́ Elotu, o si mu u pada fun Juda; lẹhin ti ọba sùn pẹlu awọn baba rẹ̀.
3. Ẹni ọdun mẹrindilogun ni Ussiah, nigbati o bẹ̀rẹ si ijọba, o si jọba ọdun mejilelãdọta ni Jerusalemu. Orukọ iya rẹ̀ si ni Jekoliah ti Jerusalemu.