2. Kro 11:4-11 Yorùbá Bibeli (YCE)

4. Bayi li Oluwa wi, ẹnyin kò gbọdọ gòke lọ, bẹ̃li ẹnyin kò gbọdọ ba awọn arakunrin nyin jà: ki olukuluku pada si ile rẹ̀: nitori ọ̀ran yi lati ọdọ mi wá ni. Nwọn si gbà ọ̀rọ Oluwa gbọ́, nwọn si yipada kuro lati lọ iba Jeroboamu.

5. Rehoboamu si ngbe Jerusalemu, o si kọ́ ilu olodi ni Juda.

6. O kọ́ Betlehemu pẹlu, ati Etamu, ati Tekoa,

7. Ati Bet-Suri, ati Soko, ati Adullamu,

8. Ati Gati, ati Mareṣa, ati Sifu,

9. Ati Adoraimu, ati Lakiṣi, ati Aseki,

10. Ati Sora, ati Aijaloni, ati Hebroni, ti o wà ni Juda ati ni Benjamini, awọn ilu olodi.

11. O si mu awọn ilu olodi lagbara, o si fi awọn balogun sinu wọn ati akojọ onjẹ, ati ororo ati ọti-waini.

2. Kro 11