2. Kro 11:2-13 Yorùbá Bibeli (YCE)

2. Ṣugbọn ọ̀rọ Oluwa tọ Ṣemaiah, enia Ọlọrun, wá, wipe,

3. Sọ fun Rehoboamu ọmọ Solomoni, ọba Juda, ati fun gbogbo Israeli ni Juda ati Benjamini, wipe,

4. Bayi li Oluwa wi, ẹnyin kò gbọdọ gòke lọ, bẹ̃li ẹnyin kò gbọdọ ba awọn arakunrin nyin jà: ki olukuluku pada si ile rẹ̀: nitori ọ̀ran yi lati ọdọ mi wá ni. Nwọn si gbà ọ̀rọ Oluwa gbọ́, nwọn si yipada kuro lati lọ iba Jeroboamu.

5. Rehoboamu si ngbe Jerusalemu, o si kọ́ ilu olodi ni Juda.

6. O kọ́ Betlehemu pẹlu, ati Etamu, ati Tekoa,

7. Ati Bet-Suri, ati Soko, ati Adullamu,

8. Ati Gati, ati Mareṣa, ati Sifu,

9. Ati Adoraimu, ati Lakiṣi, ati Aseki,

10. Ati Sora, ati Aijaloni, ati Hebroni, ti o wà ni Juda ati ni Benjamini, awọn ilu olodi.

11. O si mu awọn ilu olodi lagbara, o si fi awọn balogun sinu wọn ati akojọ onjẹ, ati ororo ati ọti-waini.

12. Ati ni olukuluku ilu li o fi asà ati ọ̀kọ si, o si mu wọn lagbara gidigidi, o si ni Juda ati Benjamini labẹ rẹ̀.

13. Ati awọn alufa ati awọn ọmọ Lefi, ti o wà ni gbogbo Israeli, tọ̀ ọ lọ lati gbogbo ibugbe wọn wá.

2. Kro 11