2. A. Ọba 15:1-4 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. LI ọdun kẹtadilọgbọ̀n Jeroboamu ọba Israeli ni Asariah (Ussiah) ọmọ Amasiah ọba Juda bẹ̀rẹ si ijọba.

2. Ẹni ọdun mẹrindilogun li on iṣe nigbati o bẹ̀rẹ si ijọba, o si jọba ọdun mejilelãdọta ni Jerusalemu. Orukọ iya rẹ̀ a ma jẹ Jekoliah ti Jerusalemu.

3. O si ṣe eyiti o tọ loju Oluwa, gẹgẹ bi gbogbo eyiti baba rẹ̀ Amasiah ti ṣe;

4. Kiki ibi giga wọnni ni a kò mu kuro: awọn enia nrubọ, nwọn si nsun turari sibẹ ni ibi giga wọnni.

2. A. Ọba 15