2. A. Ọba 1:13-15 Yorùbá Bibeli (YCE)

13. O si tun rán olori-ogun ãdọta ekẹta pẹlu ãdọta rẹ̀. Olori-ogun ãdọta kẹta si gòke, o si wá, o si wolẹ lori ẽkún rẹ̀ niwaju Elijah, o si bẹ̀ ẹ, o si wi fun u pe, Iwọ, enia Ọlọrun, emi bẹ̀ ọ́, jẹ ki ẹmi mi ati ẹmi awọn ãdọta ọmọ-ọdọ rẹ wọnyi, ki o ṣọwọn li oju rẹ.

14. Kiyesi i, iná sọ̀kalẹ lati ọrun wá, o si run olori-ogun meji arãdọta iṣãju pẹlu arãdọta wọn: njẹ nisisiyi, jẹ ki ẹmi mi ki o ṣọwọn li oju rẹ.

15. Angeli Oluwa si wi fun Elijah pe, Ba a sọ̀kalẹ lọ: máṣe bẹ̀ru rẹ̀. On si dide, o si ba a sọ̀kalẹ lọ sọdọ ọba.

2. A. Ọba 1