1. Sam 25:1-6 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. SAMUELI si kú; gbogbo enia Israeli si ko ara wọn jọ, nwọn sì sọkun rẹ̀, nwọn si sin i ninu ile rẹ̀ ni Rama. Dafidi si dide, o si sọkalẹ lọ si ijù Parani.

2. Ọkunrin kan si mbẹ ni Maoni, ẹniti iṣẹ rẹ̀ mbẹ ni Karmeli; ọkunrin na si pọ̀ gidigidi, o si ni ẹgbẹdogun agutan, ati ẹgbẹrun ewurẹ: o sì nrẹ irun agutan rẹ̀ ni Karmeli.

3. Orukọ ọkunrin na si njẹ Nabali, orukọ aya rẹ̀ si njẹ Abigaili; on si jẹ oloye obinrin, ati arẹwa enia; ṣugbọn onroro ati oniwa buburu ni ọkunrin; ẹni idile Kalebu li on si ṣe.

4. Dafidi si gbọ́ li aginju pe, Nabali nrẹ irun agutan rẹ̀.

5. Dafidi si ran ọmọkunrin mẹwa, Dafidi si sọ fun awọn ọdọmọkunrin na pe, Ẹ goke lọ si Karmeli, ki ẹ si tọ Nabali lọ, ki ẹ si ki i li orukọ mi.

6. Bayi li ẹ o si wi fun ẹniti o wà ni irọra pe, Alafia fun ọ, alafia fun ile rẹ, ati alafia fun ohun gbogbo ti iwọ ni.

1. Sam 25