1. Kro 8:1-12 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. BENJAMINI si bi Bela, akọbi rẹ̀, Aṣbeli ekeji, ati Ahara ẹkẹta,

2. Noha ẹkẹrin, ati Rafa ẹkarun.

3. Awọn ọmọ Bela ni Addari, ati Gera, ati Abihudi,

4. Ati Abiṣua, ati Naamani, ati Ahoa,

5. Ati Gera, ati Ṣefufani, ati Huramu,

6. Wọnyi si li awọn ọmọ Ehudi: wọnyi li awọn olori baba wọn, ti nwọn ngbe Geba, nwọn si ko wọn lọ si Mahanati ni igbekun.

7. Ati Naamani, ati Ahiah, ati Gera, o si ko wọn kuro, o si bi Ussa ati Ahihudi.

8. Ṣaharaimu si bi ọmọ ni ilẹ Moabu; lẹhin igbati o ti ran wọn lọ tan; Huṣimu ati Baera si li awọn aya rẹ̀.

9. Hodeṣi, aya rẹ̀ si bi, Jobabu, ati Sibia, ati Meṣa, ati Malkama fun u,

10. Ati Jeusi, ati Ṣokia, ati Mirma. Wọnyi li awọn ọmọ rẹ̀, olori awọn baba.

11. Huṣimu si bi Ahitubu ati Elpaali fun u.

12. Awọn ọmọ Elpaali, Eberi, ati Miṣamu ati Ṣameri, ẹniti o kọ́ Ono ati Lodi pẹlu ilu wọn:

1. Kro 8