1. Kro 23:1-5 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. NIGBATI Dafidi gbó, ti o si kún fun ọjọ, o fi Solomoni ọmọ rẹ̀ jẹ ọba lori Israeli.

2. O si kó gbogbo awọn ijoye Israeli jọ, ati awọn alufa ati awọn ọmọ Lefi.

3. A si ka awọn ọmọ Lefi lati ẹni ọgbọ̀n ọdun ati jù bẹ̃ lọ: iye wọn nipa ori wọn, ọkunrin kọkan sí jẹ ẹgbã mọkandilogun.

4. Ninu wọnyi, ẹgbã mejila ni lati ma bojuto iṣẹ ile Oluwa; ẹgbãta si nṣe olori ati onidajọ:

5. Ẹgbaji si jẹ adena: ẹgbaji si fi ohun-elo ti mo ṣe lati buyìn, yìn Oluwa.

1. Kro 23