1. A. Ọba 15:8-13 Yorùbá Bibeli (YCE)

8. Abijah si sùn pẹlu awọn baba rẹ̀; nwọn si sin i ni ilu Dafidi: Asa, ọmọ rẹ̀, si jọba ni ipò rẹ̀.

9. Ati li ogun ọdun Jeroboamu ọba Israeli, ni Asa jọba lori Juda.

10. Ọdun mọkanlelogoji li o jọba ni Jerusalemu, orukọ iya nla rẹ̀ si ni Maaka, ọmọbinrin Abiṣalomu.

11. Asa si ṣe eyiti o tọ loju Oluwa, bi Dafidi baba rẹ̀.

12. O si mu awọn ti nṣe panṣaga kuro ni ilẹ na, o si kó gbogbo ere ti awọn baba rẹ̀ ti ṣe kuro.

13. Ati Maaka iya rẹ̀ papã, li o si mu kuro lati ma ṣe ayaba, nitori ti o yá ere kan fun oriṣa rẹ̀; Asa si ke ere na kuro; o si daná sun u nibi odò Kidroni.

1. A. Ọba 15