Hos 8:1-4 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. FI ipè si ẹnu rẹ. Yio wá bi idì si ile Oluwa, nitori nwọn ti re majẹmu mi kọja, nwọn si ti rú ofin mi.

2. Nwọn o kigbe si mi pe, Ọlọrun mi, awa Israeli mọ̀ ọ.

3. Israeli ti gbe ohunrere sọnù; ọta yio lepa rẹ̀.

4. Nwọn ti fi ọba jẹ, ṣugbọn kì iṣe nipasẹ̀ mi: nwọn ti jẹ olori, ṣugbọn emi kò si mọ̀: fàdakà wọn ati wurà wọn ni nwọn fi ṣe òriṣa fun ara wọn, ki a ba le ké wọn kuro.

Hos 8