Gẹn 36:3-9 Yorùbá Bibeli (YCE)

3. Ati Baṣemati, ọmọbinrin Iṣmaeli, arabinrin Nebajotu.

4. Ada si bí Elifasi fun Esau; Baṣemati si bí Reueli;

5. Aholibama si bí Jeuṣi, ati Jaalamu, ati Kora: awọn wọnyi li ọmọkunrin Esau, ti a bí fun u ni ilẹ Kenaani.

6. Esau si mú awọn aya rẹ̀, ati awọn ọmọkunrin rẹ̀, ati awọn ọmọbinrin rẹ̀, ati gbogbo awọn enia ile rẹ̀, ati ẹran rẹ̀, ati gbogbo ohun-ọ̀sin, ati ohun iní gbogbo ti o ní ni ilẹ Kenaani; o si lọ si ilẹ kan kuro niwaju Jakobu arakunrin rẹ̀.

7. Nitori ti ọrọ̀ wọn pọ̀ jù ki nwọn ki o gbé pọ̀ lọ; ilẹ ti nwọn si ṣe atipo si kò le gbà wọn, nitori ohun-ọ̀sin wọn.

8. Bẹ̃ni Esau tẹ̀dó li oke Seiri: Esau ni Edomu.

9. Wọnyi si ni iran Esau, baba awọn ara Edomu, li oke Seiri:

Gẹn 36